7. “Nígbà tí mo jáde la àárin ìlú lọ síẹnu ibodè, nígbà tí mo tẹ́ ìtẹ́ mi ní ìgboro,
8. Nígbà náà ni àwọn ọmọkùnrin rími, wọ́n sì sápamọ́, àwọn àgbà dìde dúró ní ẹṣẹ̀ wọn;
9. Àwọn ọmọ aládé dákẹ́ ọ̀rọ̀ sí sọ,wọn a sì fí ọwọ́ wọn lé ẹnu;
10. Àwọn ọmọ ọlọ́lá dákẹ́, ahọ́n wọnsì lẹ̀mọ́ èrìgì ẹnu wọn.
11. Nígbà tí etí gbọ́, ó sì súrefún mi,àti nígbà tí ojú sì rí mi, ó jẹ́rìí mi;
12. Nítorí mo gbà talákà tí n fẹ́ ìrànlọ́wọ́,àti aláìní baba, tí kò sí olùrànlọ́wọ́ fún un
13. Ẹni tí ó ń kìlọ̀ súre fún mi, èmisì mú àyà opó kọrin fún ayọ̀.
14. Èmi sì mú òdodo wọ̀ bí aṣọ, ẹ̀tọ́mi dà bí aṣọ ìgúnwà àti adé ọba.
15. Mo ṣe ojú fún afọ́jú mo sì ṣe ẹṣẹ̀fún amúkùnún.
16. Mo ṣe baba fún talákà, mo ṣeìwádìí ọ̀ràn àjòjì tí èmi kò mọ̀ rí.
17. Mo sì ká eyín ẹ̀rẹ̀kẹ́ ìkà ènìyàn,mo sì já ohun ọdẹ náà kúrò ní eyín rẹ̀.
18. “Nígbà náà ni mo rò pé, ‘Èmi yóòkú nínú ilé mi, èmi yóò sì mú ọjọ́ mi pọ̀ sí i bí i yanrìn.
19. Gbòǹgbò mi yóò ta kan omi, ìrìyóò sì sẹ̀ ní gbogbo òru sí ara ẹ̀ka mi.
20. Ògo mi yóò wà ní ọ̀tún ní ọ̀dọ̀mi, ọrun mi sì padà di titun ní ọwọ́ mi’