Jóòbù 29:20-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Ògo mi yóò wà ní ọ̀tún ní ọ̀dọ̀mi, ọrun mi sì padà di titun ní ọwọ́ mi’

21. “Èmi ni ènìyàn ń dẹtí sílẹ̀ sí, wọna sì dúró, wọn a sì dákẹ́ rọ́rọ́ ní ìmọ̀ràn mi.

22. Lẹ́yìn ọ̀rọ̀ mi, wọn kò tún sọ̀rọ̀mọ́; ọ̀rọ̀ mi wọ̀ wọ́n ní etí ṣinṣin.

23. Wọn a sì dúró dè mí bí ẹni wí péwọ́n dúró fún ọ̀wọ́ òjò wọn a sìmu nínú ọ̀rọ̀ mi bí ẹní mu nínú òjò àrọ̀-kúrò.

24. Èmi sì rẹ́rìn ín sí wọn nígbà tí wọnkò bá gbà á gbọ́; ìmọ́lẹ̀ ojú mi jẹ́ iyebíye síwọn.

25. Mo la ọ̀nà sílẹ̀ fún wọn, mo sìjókòó bí olóyè wọn; mo jókòó bíọba ní àárin ológun rẹ̀; mo sìrí bí ẹni tí ń tu ẹni tí ń sọ̀fọ̀ nínú.

Jóòbù 29