Jóòbù 28:9-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé akọ òkúta, ó yí òkèńlá po láti ìdí rẹ̀ wá.

10. Ó sì la ipa odò ṣíṣàn nínú àpáta,ojú inú rẹ̀ sì rí ohun iyebíye gbogbo.

11. Ó sì ṣe ìṣàn odò kí ó má ṣe kún—kún-ya, ó sì mú ohun tí ópamọ́ hàn jáde wá sí ìmọ́lẹ̀.

12. “Ṣùgbọ́n níbo ni á ó gbé wáọgbọ́n rí, níbo sì ni òye ń gbe?

13. Ènìyàn kò mọ iye rẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni a kò le è rí i ní ilẹ̀ àwọn alààyè.

14. Ọ̀gbun wí pé, kò sí nínú mi;omi òkun sì wí pé, kò si nínú mi.

15. A kò le è fi wúrà rà á, bẹ́ẹ̀ ni a kòle è fi òsùnwọ̀n wọn fàdákà ní iye rẹ̀.

Jóòbù 28