Jóòbù 19:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ígbà náà ni Jóòbù dáhùn, ó sì wí pé:

2. “Yóò ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin ó fi máa fi ìyàjẹ mí, tí ẹ̀yin ó fi máa fi ọ̀rọ̀ mi ní ìjàǹjá?

3. Ìgbà mẹ́wàá ní ẹ̀yin ti ń gàn mí;ojú kò tìyín tí ẹ fi jẹ mí níyà.

4. Kí a sì wí bẹ́ẹ̀ pé, mo sìnà nítòótọ́,ìsìnà mi wà lára èmi tìkáarami.

5. Bí ó tilẹ̀ ṣe pé ẹ̀yin ó ṣògo si milórí nítòótọ́, tí ẹ ó sì máa fi ẹ̀gàn mi gún mí lójú,

6. Kí ẹ mọ̀ nísinsin yìí pé, Ọlọ́run ni óbì mí ṣubú, ó sì nà àwọ̀n rẹ̀ yí mi ká.

Jóòbù 19