6. “Bí èmi tilẹ̀ sọ̀rọ̀, ìbìnújẹ́ mi kò tù;bí mo sì tilẹ̀ dákẹ́, níbo ni ìtùnú mí dé?
7. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó dá milágara; Ìwọ (Ọlọ́run) mú gbogbo ẹgbẹ́ mi takété.
8. Ìwọ sì fi ìkiyẹ̀jẹ kùn mí lára, tí ójẹ́rìí tì mí; àti rírù tí ó yọ lára mi, ó jẹ́rìí lòdì sí ojú mi.
9. Ọlọ́run fi Ìbínú rẹ̀ fà mí ya, ósì ṣọ̀tá mi; ó pa eyín rẹ̀ keke sími, ọ̀ta mi sì gbójú rẹ̀ sí mi.