9. Kí ni ìwọ mọ̀ tí àwa kò mọ̀? Òyekí ní ó yé ọ tí kò sí nínú wa?
10. Eléwú ogbó àti ògbólógbòóènìyàn wà pẹ̀lú wa, tí wọ́n gbójú baba rẹ lọ.
11. Ìtùnú Ọlọ́run ha kéré lọ́dọ̀ rẹ?Ọ̀rọ̀ kan sì ṣe jẹ́jẹ́ jù lọ́dọ̀ rẹ?
12. Èéṣe ti àyà rẹ fi ń dà ọ kiri,kí ni n mú ojú rẹ se wàìwàì.
13. Tí ìwọ fi yí ẹ̀mí rẹ padà lòdì síỌlọ́run, tí ó fi ń jẹ́ ki ọ̀rọ̀kọ́rọ̀kí ó máa bọ́ ní ẹnu rẹ̀ bẹ́ẹ̀?
14. “Kí ni ènìyàn tí ó fi mọ́? Àti ẹni tía tinú obìnrin bí tí yóò fi ṣe olódodo?
15. Kíyèsí i, òun (Ọlọ́run) kògbẹ́kẹ̀lé àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀,àní àwọn ọ̀run kò mọ́ ní ojú rẹ̀;
16. Ańbọ̀tórí ènìyàn, ẹni ìríra àtieléèérìí, tí ń mù ẹ̀ṣẹ̀ bi ẹní mú omi.
17. “Èmi ó fihàn ọ́: gbọ́ ti èmi; Èyí tíèmi sì rí, òun ni èmi ó sì sọ,
18. tí àwọn ọlọ́gbọ́n ti pa ní ìtàn latiọ̀dọ̀ àwọn baba wọn wá, ti wọ́n kò sì fi pamọ́,
19. Àwọn tí a fi ilẹ̀ ayé fún nìkan,àlejò kan kò sì là wọ́n kọjá.
20. Ènìyàn búburú ń ṣe làálàá, pẹ̀lúìrora, ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo, àti iyeọdún ní a dá sílẹ̀ fún aninilára.
21. Ìró ìbẹ̀rù ń bẹ ní etí rẹ̀;nínú ìrora ni apanirun yóò dìde sí i.
22. O kò gbàgbọ́ pé òun ó jáde kúrònínú òkùnkùn; a sì ṣà á sápákan fún idà.
23. Ó ń wò káàkiri fún oúnjẹ wí pé,níbo ní ó wà? Ó mọ̀ pé ọjọ́òkùnkùn súnmọ́ tòsí.
24. Ìpọ́njú pẹ̀lú ìrora ọkàn yóò mú unbẹ̀rù, wọ́n ó sì sẹ́gun rẹ̀ bi ọba ti ímúra ogun.
25. Nítorí pé ó ti nawọ́ rẹ̀ jáde lòdìsí Ọlọ́run, ó sì múra rẹ̀ le lòdì sí Olódùmáarè,
26. Ó súre, ó sì fi ẹ̀yìn giga, àní fiìké kòóko àpáta rẹ̀ tí ó nipọn kọlù ú.
27. “Nítorí tí òun fi ọ̀rá rẹ̀ bo ara rẹ̀lojú, o sì ṣe jabajaba ọ̀rá sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀.
28. Òun sì gbé inú ahoro ìlú ìtakété,àti nínú iléyílé tí ènìyàn kò gbémọ́, tí ó múra tán lati di àlàpà.
29. Òun kò lé ìlà, bẹ́ẹ̀ ohun ìní rẹ̀ kòlè dúró pẹ́; Bẹ́ẹ̀ kò lè mú pípé rẹ̀ dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.