Jóòbù 13:13-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. “Ẹ pa ẹnu yín mọ́ kúrò lára mi,kí èmi kí ó lè sọ̀rọ̀, ohun tí ńbọ̀ wá íbá mi, kí ó máa bọ̀.

14. Ǹjẹ́ nítorí kí ni èmi ṣe ń fi èyín mibu ẹran ara mi jẹ, Tí mo sì gbé ẹ̀mí mi lé ara mi lọ́wọ́?

15. Bí ó tilẹ̀ pa mí, síbẹ̀ èmi ó máa gbẹ́kẹ̀lé e;Ṣùgbọ́n èmi ó máa tẹnumọ́ ọ̀nà mi níwájú rẹ̀.

16. Èyí ni yóò sì ṣe ìgbàlà mi,Àgàbàgebè kì yóò wá síwájú rẹ̀.

17. Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu mi ní ìfàyàbalẹ̀, àti àṣọpé mí ni etí yín.

18. Wò ó nísinsin yìí, èmi ti làdí ọ̀ran mi sílẹ̀;èmi mọ̀ pé a ó dá mi láre.

19. Ta ni òun ti yóò bá mi ṣàròyé?Ǹjẹ́ nísinsìn yìí, èmi fẹ́ pa ẹnu mí mọ́, èmi ó sì jọ́wọ́ ẹ̀mi mi lọ́wọ́.

20. “Ṣùgbọ́n, má ṣe ṣe ohun méjì yìí sí mi,Nígbà náà ni èmi kì yóò sì fi ara mi pamọ́ kúrò fún ọ:

Jóòbù 13