Jòhánù 7:48-51 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

48. Ǹjẹ́ nínú àwọn ìjòyè, tàbí àwọn Farisí ti gbà á gbọ́ bí?

49. Ṣùgbọ́n ìjọ ènìyàn yìí, tí ko mọ òfin di ẹni ìfibú.”

50. Nikodémù ẹni tí ó tọ Jésù wá lóru rí, tí ó sì jẹ́ ọ̀kan nínú wọn sì sọ fún wọn pé,

51. “Òfin wa ha ń ṣe ìdájọ́ ènìyàn kí ó tó gbọ́ ti ẹnu rẹ̀ àti kí ó tó mọ ohun tí ó ṣe bí?”

Jòhánù 7