23. Ṣùgbọ́n àkókò ń bọ̀, ó sì dé tán nísinsìn yìí, nígbà tí àwọn olùsìn tòótọ́ yóò máa sin Baba ní ẹ̀mí àti ní òtítọ́: nítorí irú wọn ni Baba ń wá kí ó máa sin òun.
24. Ẹ̀mí ni Ọlọ́run: àwọn ẹni tí ń sìn ín kò lè ṣe aláìsìn ín ní ẹ̀mí àti ní òtítọ́.”
25. Obìnrin náà wí fún un pé, mo mọ̀ pé, “Mèsáyà ń bọ̀ wá, tí a ń pè ní Krísítì: Nígbà tí Òun bá dé, yóò sọ ohun gbogbo fún wa.”
26. Jésù sọ ọ́ di mímọ̀ fún un pé, “Èmi ẹni tí ń bá ọ sọ̀rọ̀ yìí ni Òun.”