26. Nítorí náà Jésù dáhùn pé, “Òun náà ni, ẹni tí mo bá fi àkàrà fún nígbà tí mo bá fi run àwo.” Nígbà tí ó sì fi run ún tan, ó fi fún Júdásì Ísíkárótù ọmọ Símónì.
27. Ní kété tí Júdásì gba àkàrà náà ni Sátanì wọ inú rẹ̀ lọ.Nítorí náà Jésù wí fún un pé, “Ohun tí ìwọ ń se nì, yára ṣe é kánkán.”
28. Kò sì sí ẹnìkan níbi tábìlì tí ó mọ ìdí tí ó ṣe sọ èyí fún un.
29. Nítorí àwọn mìíràn nínú wọn rò pé, nitorí Júdásì ni ó ni àpò, ni Jésù fi wí fún un pé, Ra nǹkan wọ̀n-ọn-nì tí a kò le ṣe aláìní fún àjọ náà; tàbí kí ó lè fi nǹkan fún àwọn talákà.
30. Nígbà tí ó sì ti gbà òkèlè náà tan, ó jáde lójúkan náà: òru sì ni.
31. Nítorí náà nígbà tí ó jáde lọ tan, Jésù wí pé, “Nísinsìn yìí ni a yin ọmọ-ènìyàn lógo, a sì yin Ọlọ́run lógo nínú rẹ̀.