12. “Ẹ jí, ẹ sì gòkè wá sí àfonífojìJéhóṣáfátì ẹ̀yin aláìkọlà:nítorí níbẹ̀ ní èmi yóò jòkòó láti ṣeìdájọ́ àwọn aláìkọlà yí kákìri.
13. Ẹ tẹ̀ dòjé bọ̀ ọ́,nítorí ìkórè pọ́n:ẹ wá, ẹ ṣọ̀kalẹ̀;nítorí ìfúntí kún, nítorí àwọnọpọ́n kún-à-kún-wọ́sílẹ̀nítorí ìwà búburú wọn pọ̀!”
14. Ọ̀pọ̀lọpọ̀, ọ̀pọ̀lọpọ̀ní àfonífojì ìdájọ́,nítorí ọjọ Olúwa kù si dẹ̀dẹ̀ní àfonífojì ìdájọ́.
15. Oòrùn àti òṣùpá yóò ṣú òkùnkùn,àti àwọn ìràwọ̀ kí yóò tan ìmọ́lẹ̀ wọn mọ́.