29. Àti pẹ̀lú sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin,àti sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ obìnrin,ní èmi yóò tú ẹ̀mi mí jáde ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì.
30. Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu hàn ní ọrunàti ní àyé,ẹ̀jẹ̀ àti iná, àti ọ̀wọ́n èéfín.
31. A á sọ oòrùn di òkùnkùn,àti òṣùpá di ẹ̀jẹ̀,kí ọjọ́ ńlá àti ọjọ́ ẹ̀ru Olúwa tó dé.
32. Yóò sí ṣe ẹnikẹ́ni tí ó ba ké pèorúkọ Olúwa ní a ó gbàlà:nítorí ní òkè Ṣíónì àti ní Jérúsálẹ́mùní ìgbàlà yóò gbé wà,bí Olúwa ti wí,àti nínú àwọnìyókù tí Olúwa yóò pè.