Jóẹ́lì 1:5-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Ẹ jí gbogbo ẹ̀yín ọ̀mùtí kí ẹ sì ṣunkúnẹ pohùnréré ẹkún gbogbo ẹ̀yinọ̀mu-wáìnì; ẹ pohùnréré ẹkún nítorí wáìnì tuntunnítorí a gbà á kúrò lẹ́nu yín.

6. Nítorí orílẹ̀ èdè kan ti sígun sí ilẹ̀ mìírànó ní agbára púpọ̀, kò sì ní òǹkà;ó ní eyín kìnnìúnó sì ní èrìgì abo kìnnìún.

7. Ó ti pa àjàrà mi run,ó sì ti ya ẹ̀ka igi ọ̀pọ̀tọ́ mi kúrò,ó ti bò èèpo rẹ̀ jálẹ̀, ó sì sọ ọ́ nù;àwọn ẹ̀ka rẹ̀ ni a sì sọ di fun-fun.

8. Ẹ pohùnréré ẹkún bí wúndíátí a fi aṣọ ọ̀fọ̀ dí ni àmúre, nítorí ọkọ ìgbà èwe rẹ̀.

9. A ké ọrẹ jíjẹ́ àti ọrẹ mímú kúròní ilé Olúwa;àwọn àlùfáà ń ṣọ̀fọ̀, àwọnìrànṣẹ́ Olúwa,

10. Oko di ìgboro, ilẹ̀ ń sọ̀fọ̀ nítorí,a fi ọkà ṣòfò:ọtí wáìnì tuntún gbé, òróró ń bùṣe.

11. Kí ojú kí ó tì yín, ẹ̀yin àgbẹ̀;ẹ pohùn réré ẹkún ẹ̀yin olùtọ́jú àjàrà,nítorí àlìkámà àti nítorí ọkà báálì;nítorí ìkórè oko ṣègbé.

Jóẹ́lì 1