Jeremáyà 52:5-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Ìlú náà sì wá lábẹ́ ìhámọ́ títí di ọdún kọkànlá Ọba Sédékáyà.

6. Ní ọjọ́ kẹ́sàn án, oṣù mẹ́rin ìyàn ìlú náà sì ti burú dé ibi pé kò sí oúnjẹ kankan mọ́ fún àwọn ènìyàn láti jẹ.

7. Bákan náà, odi ìlú náà ti ya àwọn ọmọ ogun sì tí sálọ. Wọn fi ìlú náà sílẹ̀ ní òru nípa ojú ọ̀nà tó wà láàrin odi méjèèjì lẹ́bàá ọgbà Ọba. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, Àwọn ará Bábílónì yìí yí ìlú náà ká. Wọ́n sá gba aginjù lọ.

8. Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ogun Bábílónì lépa Ọba Sedekáyà wọ́n sì le bá ni pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jẹ́ríkò. Gbogbo àwọn ọmọ ogun sì pínyà, kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ wọ́n sì túká.

9. Wọ́n sì mu ní ìgbèkùn. Wọn mú un lọ sí ọ̀dọ̀ Ọba Bábílónì, ní Ríbíla ní ilẹ̀ Hámátì níbẹ̀ ni ó ti ṣe ìdájọ́ lórí rẹ̀.

Jeremáyà 52