51. “Ojú tì wá, nítorí pé àwa ti gbọ́ ẹ̀gàn:ìtìjú ti bò wá lójúnítorí àwọn àlejò wá sórí ohun mímọ́ ilé Olúwa.”
52. “Nítorí náà, wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí,“tí èmi yóò se ìbẹ̀wò lórí àwọn ère fífin rẹ̀:àti àwọn tí ó gbọgbẹ́ yóò sì máa gbin já gbogbo ilẹ̀ rẹ̀
53. Bí Bábílónì tilẹ̀ gòkè lọ sí ọ̀run,bí ó sì ṣe ìlú olodi ní òkè agbára rẹ,síbẹ̀ àwọn afiniṣèjẹ yóò ti ọ̀dọ̀ mi tọ̀ ọ́ wá,”ní Olúwa wí.
54. “Ìró igbe láti Bábílónì,àti ìparun láti ilẹ̀ àwọn ará Kálídéà!
55. Nítorí pé Olúwa ti ṣe Bábílónì ní ìjẹ,ó sì ti pa ohun ńlá run kúrò nínú rẹ̀;rírú wọn sì ń hó bi púpọ̀, a gbọ́ ariwo ohùn wọn.