Jeremáyà 5:21-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Gbọ́ èyí, ẹ̀yin aláìlóye àti aláìlọ́gbọ́n ènìyàn,tí ó lójú ti kò fi rírantí ó létí ti kò fi gbọ́ran.

22. Kò ha yẹ kí ẹ bẹ̀rù mi?” ni Olúwa wí.“Kò ha yẹ kí èyin ó wárìrì níwájú mi bí?Mo fi yanrìn pààlà òkun,èyí tí kò le è rékọjá rẹ̀ láéláé.Ìjì lè jà, kò le è borí rẹ̀;wọ́n le è bú, wọn kò le è rékọjá rẹ̀.

23. Ṣùgbọ́n, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọkàn líle àti ọkàn ọ̀tẹ̀,wọ́n ti yípadà, wọ́n sì ti lọ.

Jeremáyà 5