Jeremáyà 49:6-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. “Olúwa àwọn ọmọ ogun.Gbogbo yín ni ó lé jáde, kò sì sí ẹnìkantí yóò dá ìkólọ Ámónì padà,”ni Olúwa wí.

7. Nípa Édómù:Èyí ní ohun tí Olúwa àwọn ọmọ ogun wí:“Ṣe kò ha sí ọgbọ́n mọ́ ni Temánì?Ṣé a ti ké ìmọ̀ràn kúrò ní ọ̀dọ̀ olóyè?Ṣé ọgbọ́n wọn ti bàjẹ́ bí?

8. Yípadà kí o sálọ, sá pamọ́ sínú ihò,ìwọ tí ó ń gbé níDédánì nítorí èmi yóò múibi wá sórí Ísọ̀ ní àkókò tí èmi ó fìyà jẹ́ẹ́.

9. Tí àwọn tí ń ṣa èso bá tọ̀ ọ́ wá;ǹjẹ́ wọn kò ní fi èso díẹ̀ sílẹ̀?Tí olè bá wá ní òru; ǹjẹ́ wọn kò níkó gbogbo ohun tí wọ́n bá fẹ́?

10. Ṣùgbọ́n èmi yóò tu Ísọ̀ sí ìhòòhòèmi kò ní bo ibi ìkọ̀kọ rẹnítorí kí o máa baà fi ara rẹ pamọ́.Àwọn ọmọ rẹ, ẹbí rẹ àtiàwọn ará ilé rẹ yóò parun.Wọn kò sì ní sí mọ́.

Jeremáyà 49