Jeremáyà 49:24-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Dámásíkù di aláìlera, ó pẹ̀yindàláti sálọ, ìwárìrì sì dé bá a,ìbẹ̀rù àti ìrora dì í mú, ìrorabí ti obìnrin tí ó wà ní ipò ìrọbí.

25. Kí ló dé tí ìlú olókìkí di ohun ìkọ̀sílẹ̀;ìlú tí mo dunnú sí.

26. Lóòtọ́, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin rẹyóò ṣubú lójú pópó, gbogboàwọn ọmọ ogun rẹ yóò paẹnu mọ́ ní ọjọ́ náà,”ní Olúwa àwọn ọmọ ogun wí.

27. “Èmi yóò fi iná sí odi Dámásíkù,yóò sì jó gbọ̀ngàn Bẹni-hádádì run.”

28. Nípa Kédárì àti ìjọba Ásọ́rì èyí ti Nebukadinésárì Ọba Bábílónì dojú ìjà kọ:Èyí ni ohun tí Olúwa sọ:“Dìde kí o sì dojú ìjà kọ kédárì,kí o sì pa àwọn ènìyàn ìlà oòrùn run.

Jeremáyà 49