Jeremáyà 49:22-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

22. Wò ó! Ẹyẹ idì yóò gòkè fò wálẹ̀,yóò tẹ ìyẹ́ rẹ̀ lórí Bóráṣà.Ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn ajagunÉdómù yóò dàbí ọkan obìnrin tí ń rọbí.

23. Nípa Dámásíkù:“Inú Hámátì àti Árípádì bàjẹ́ nítorí wọ́n gbọ́ ìròyìn búburú, ìjayà dé bá wọn,wọ́n sì dààmú bí omi òkun.

24. Dámásíkù di aláìlera, ó pẹ̀yindàláti sálọ, ìwárìrì sì dé bá a,ìbẹ̀rù àti ìrora dì í mú, ìrorabí ti obìnrin tí ó wà ní ipò ìrọbí.

25. Kí ló dé tí ìlú olókìkí di ohun ìkọ̀sílẹ̀;ìlú tí mo dunnú sí.

26. Lóòtọ́, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin rẹyóò ṣubú lójú pópó, gbogboàwọn ọmọ ogun rẹ yóò paẹnu mọ́ ní ọjọ́ náà,”ní Olúwa àwọn ọmọ ogun wí.

27. “Èmi yóò fi iná sí odi Dámásíkù,yóò sì jó gbọ̀ngàn Bẹni-hádádì run.”

Jeremáyà 49