Jeremáyà 47:3-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Nígbà tí wọ́n bá gbọ́ ìró títẹlẹ̀ pátakò ẹsẹ̀ ẹṣin alágbáranígbà tí wọ́n bá gbọ́ ariwo kẹ̀kẹ́ ogun ọ̀tá ńláàti iye kẹ̀kẹ́ wọn.Àwọn baba kò ní lè ran àwọn ọmọ lọ́wọ́;ọwọ́ wọn yóò kákò.

4. Nítorí tí ọjọ́ náà ti péláti pa àwọn Fílístínì run,kí a sì mú àwọn tí ó làtí ó lè ran Tírè àti Sídónì lọ́wọ́ kúrò. Olúwa ti ṣetán láti pa Fílístínì run,àwọn tí ó kù ní agbègbè Káfútò.

5. Gásà yóò fá irun orí rẹ̀ nínú ọ̀fọ̀.A ó pa Áṣíkélónì lẹ́nu mọ́;ìyókù ní pẹ̀tẹ́lẹ̀,ìwọ yóò ti ṣá ara rẹ lọ́gbẹ́ pẹ́ tó?

6. “Ẹ̀yin kígbe, ‘Yé è, idà Olúwa,yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò sinmi?Padà sínú àkọ̀ re;sinmi kí o sì dákẹ́ jẹ́ẹ́.’

Jeremáyà 47