6. Ìbá à ṣe rere, ìbá à ṣe búburú, àwa yóò gbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run wa; èyí tí àwa ń rán ọ sí; Kí ó ba à lè dára fún wa. Nítorí pé àwa yóò gbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run wa.”
7. Lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́wàá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremáyà wá wí pé;
8. Nígbà náà ni a ó pa Jóhánánì ọmọkùnrin Káréà àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀; àti gbogbo àwọn ènìyàn láti orí ẹní tí ó kéré dé orí ẹni ńlá.
9. Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Ísírẹ́lì wí: ‘Èyí ni ẹni tí ẹ̀yin ti rán láti gbé ẹ̀bẹ̀ yín lọ ṣíwájú mi.
10. Bí ẹ̀yin bá gbé ní ilẹ̀ yìí, èmi yóò gbé e yín ró, n kò sí ní fà yín lulẹ̀, èmi yóò gbìn yín, n kì yóò fà yín tu nítorí wí pé èmi yí ọkan padà ní ti ibi tí mo ti ṣe sí i yín.