Jeremáyà 4:23-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

23. Mo bojú wo ayé,ó sì wà ní júujùu, ó sì ṣófoàti ní ọ̀run,ìmọ́lẹ̀ wọn kò sì sí.

24. Mo wo àwọn òkè ńlá,wọ́n wárìrì;gbogbo òkè kékèké mì jẹ̀jẹ̀.

25. Mo wò yíká n kò rí ẹnìkan;gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ló ti fò lọ.

26. Mo bojú wò, ilẹ̀ eléṣo, ó sì di aṣálẹ̀gbogbo àwọn ìlú inú rẹ̀ sì ṣubú sínú ìparunníwájú Olúwa àti níwájú ríru ìbínú rẹ̀.

27. Èyí ni ohun tí Olúwa wí“Gbogbo ìlú náà yóò sì di ahoro,síbẹ̀ èmi kì yóò pa á run pátapáta.

28. Nítorí náà, ayé yóò pohùnréré ẹkúnàwọn ọ̀run lókè yóò ṣóòkùnnítorí mo ti sọ, mo sì ti pète rẹ̀mo ti pinnu, n kì yóò sì yí i padà.”

29. Nípa ariwo àwọn ẹlẹ́ṣin àti àwọn tafàtafàgbogbo ìlú yóò sálọ.Ọ̀pọ̀ sálọ sínú igbó;ọ̀pọ̀ yóò sì gun orí àpáta lọ.Gbogbo ìlú náà sì di ahoro;kò sì sí ẹnìkan nínú rẹ̀.

Jeremáyà 4