18. Nígbà náà, Jeremáyà sọ fún Ọba Sedekáyà pé, “Irú ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ yín, àwọn ìjòyè yín pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí ẹ fi sọ mí sínú túbú?
19. Níbo ni àwọn wòlíì yín tí wọ́n ń sọ àṣọtẹ́lẹ̀ fún-un yín wí pé Ọba Bábílónì kò ní gbógun tì yín wá?
20. Ṣùgbọ́n ní báyìí, Olúwa mi Ọba jọ̀wọ́ gbọ́. Jẹ́ kí n mú ẹ̀dùn ọkàn mi tọ̀ ọ́ wá; má ṣe rán mi padà sí ilé Jónátanì akọ̀wé, à fi kí n kú síbẹ̀.”
21. Ọba Sedekáyà wá pàṣẹ pé kí wọ́n fi Jeremáyà sínú àgbàlá àwọn ẹ̀ṣọ́, àti kí wọn sì fún ní àkàrà ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan títí tí àkàrà yóò fi tán; bẹ́ẹ̀ ni Jeremáyà wà nínú àgbàlá náà.