Jeremáyà 23:20-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Ìbínú Olúwa kì yóò yẹ̀títí tí yóò sì fi mú èrò rẹ̀ ṣẹ,ní àìpẹ́ ọjọ́, yóò yé e yín yékéyéké.

21. Èmi kò rán àwọn wòlíì wọ̀nyísíbẹ̀ wọ́n lọ pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọn.Èmi kò tilẹ̀ bá wọn sọ̀rọ̀,síbẹ̀ wọ́n sọ àṣọtẹ́lẹ̀,

22. Ṣùgbọ́n ìbáṣepọ̀ wọn dúró nínú ìgbìmọ̀ mi,wọn ì bá ti kéde ọ̀rọ̀ mi fún àwọn ènìyàn mi.Wọn ì bá ti wàásù ọ̀rọ̀ mi sí àwọn ènìyànwọn ìbá ti yípadà kúrò nínú ọ̀nààti ìṣe búburú wọn.

23. “Ǹjẹ́ Ọlọ́run tòsí nìkan ni Èmi bí?”ni Olúwa wí,“kì í sì í ṣe Ọlọ́run ọ̀nà jínjìn.

24. Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè sá pamọ́ sí ibi kọ́lọ́fín kan,kí èmi má ba a rí?”ni Olúwa wí.“Ǹjẹ́ èmi kò há a kún ọ̀run àti ayé bí?”ni Olúwa wí.

Jeremáyà 23