Jeremáyà 19:10-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. “Nígbà náà ni ìwọ yóò fọ́ ìkòkò náà ní oju àwọn tí ó bá ọ lọ.

11. Kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ ogun wí. Èmi a fọ́ orílẹ̀ èdè yìí àti ìlú yìí gẹ́gẹ́ bí ìkòkò amọ̀ yìí ṣe fọ́ tí kò sì ní sí àtúnṣe. Wọn a sì sin àwọn òkú sí Tófẹ́tì títí tí kò fi ní sí àyè mọ́.

12. Èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí ibí yìí àti àwọn tí ń gbé ní ibí yìí ni Olúwa wí. Èmi yóò mú ìlú yìí dàbí Tófẹ́tì.

13. Àwọn ilé tí ó wà ní Jérúsálẹ́mù àti ti Ọba ìlú Júdà ni a ó sọ di àìmọ́ gẹ́gẹ́ bí ti ibí yìí ní Tófẹ́tì gbogbo ilé tí wọ́n ti ń sun tùràrí ni orí àjà sí gbogbo ènìyàn tí ó sì ń da ọtí gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí Ọlọ́run mìíràn.’ ”

Jeremáyà 19