Jeremáyà 18:17-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Gẹ́gẹ́ bí afẹ́fẹ́ láti ìlà oorùn,Èmi yóò tú wọn ká lójú àwọn ọ̀tá wọn.Èmi yóò sì kọ ẹ̀yìn sí wọn, n kì yóò kọjú sí wọnní ọjọ́ àjálù wọn.”

18. Wọ́n sọ wí pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ ṣọ̀tẹ̀ sí Jeremáyà, nítorí òfin ikọ́ni láti ẹnu àwọn àlùfáà kì yóò já sí asán, tàbí ìmọ̀ràn fún àwọn ọlọ́gbọ́n tàbí ọ̀rọ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì. Nítorí náà wá, ẹ jẹ́ kí a kọlùú pẹ̀lú ahọ́n wa, kí a má sì ṣe tẹ́tí sí ohun kóhun tí ó bá sọ.”

19. Dẹtí sí ọ̀rọ̀ mi Olúwa, gbọ́ ohuntí àwọn tí ó fi mí sùn ń sọ.

20. Ṣe kí a fi rere san búburú?Síbẹ̀ wọ́n ti gbẹ́ kòtò fún mi,rántí pé mo dúró níwájú rẹ,mo sì sọ̀rọ̀ ní torí wọn, látiyí ìbínú rẹ kúrò lọ́dọ̀ wọn.

21. Nítorí náà, jẹ́ kí ìyàn mú ọmọ wọnjọ̀wọ́ wọn fún ọwọ́ idàjẹ́ kí ìyàwó wọn aláìlọ́mọ àti opójẹ́ kí a pa àwọn ọkùnrin wọnkí a sì fi idà pa àwọn ọdọ́mọkùnrinwọn lójú ogun.

22. Jẹ́ kí a gbọ́ ohùn ẹkún láti ilé wọnnígbà tí ó bá mu àwọn jagunjagunkọ lù wọ́n lójijì nítorí wọ́n ti gbẹ́kòtò láti mú mi. Wọ́n ti dẹ ìkẹkùn fún ẹṣẹ̀ mi

Jeremáyà 18