Jeremáyà 1:4-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé,

5. Kí ó tó di pé mo dá ọ láti inú ni mo ti mọ̀ ọ́,kí ó sì tó di pé a bí ọ ni mo ti yà ọ́ sọ́tọ̀.Mo yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí wòlíì fún àwọn orílẹ̀ èdè.

6. Mo sọ pé Háà! Olúwa tí ó pọ̀ ní ipá, ọmọdé ni mí, èmi kò mọ bí a ṣe é sọ̀rọ̀.

7. Olúwa sọ fún mi pé, má ṣe sọ pé ọmọdé lásán ni mí. O gbọdọ̀ ní láti lọ sí ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tí mo rán ọ sí, kí o sì sọ ohun tí mo pa láṣẹ fún ọ.

8. Olúwa sì wí pé má ṣe bẹ̀rù wọn, nítorí tí èmi wà pẹ̀lú rẹ èmi ó sì gbà ọ́.

9. Olúwa sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi kàn mí lẹ́nu, ó sì wí fún mi pé nísinsìnyìí mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí inú ẹnu rẹ

Jeremáyà 1