Jẹ́nẹ́sísì 8:9-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Ṣùgbọ́n àdàbà náà kò rí ìyàngbẹ ilẹ̀ bà lé nítorí omi kò tí ì tan lórí ilẹ̀, ó sì padà sọ́dọ̀ Nóà. Nóà na ọwọ́ rẹ̀ jáde ó sì mú ẹyẹ náà wọlé sọ́dọ̀ ara rẹ̀ nínú ọkọ̀.

10. Ó sì dúró fún ọjọ́ méje sí i; ó sì tún rán àdàbà náà jáde láti inú ọkọ̀.

11. Nígbà tí àdàbà náà padà sọ́dọ̀ rẹ̀ ní àsáálẹ́, ó já ewé igi ólífì tútù há ẹnu! Nígbà náà ni Nóà mọ̀ pé omi ti ń gbẹ kúrò lórí ilẹ̀.

12. Nóà tún mú sùúrù fún ọjọ́ méje, ó sì tún rán àdàbà náà jáde, ṣùgbọ́n àdàbà náà kò padà sọ́dọ̀ rẹ̀ mọ́.

13. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, ní ọdún kọ́kànlélẹ́gbẹ̀ta (601) ni omi náà gbẹ kúrò lórí ilẹ̀; Nóà sì sí ọkọ̀, ó sì ri pé ilẹ̀ ti gbẹ.

14. Ní ọjọ́ kẹtàdínlọ́gbọ̀n oṣù kejì, ilẹ̀ ti gbẹ pátapáta.

15. Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Nóà pé.

Jẹ́nẹ́sísì 8