Jẹ́nẹ́sísì 49:9-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Ọmọ kìnnìún ni ọ́, ìwọ Júdà,o darí láti ìgbẹ́ ọdẹ, ọmọ mi.Bí i kìnnìún, o ba mọ́lẹ̀, o sì sùn sílẹ̀ bí i abo kìnnìún,Ta ni ó tó bẹ́ẹ̀, kí o lé e dìde?

10. Ọ̀pá oyè kì yóò kúrò ní Júdàbẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá-ìsàkóso kì yóò kúròláàrin ẹṣẹ̀ rẹ̀, títí tí ẹni tí ó ni í yóò fi dé,tí gbogbo àwọn orílẹ̀ èdè yóò máa wárí fún un.

11. Yóò má ṣo ọmọ ẹsin rẹ̀ mọ́ igi àjàrà àtiọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ mọ́ ẹ̀ka tí ó dára jù.Yóò fọ aṣọ rẹ̀ nínú wáìnì àti ẹ̀wùrẹ̀ nù nínú omi-pupa ti eṣo àjàrà (gíréèpù).

12. Ojú rẹ̀ yóò rẹ̀ dòdò ju wáìnì lọ,ẹyín rẹ yóò sì funfunu pẹ̀lú omi-ọyàn

Jẹ́nẹ́sísì 49