Jẹ́nẹ́sísì 47:4-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Wọ́n sì tún sọ fun un síwájú sí i pé, “A wá láti gbé ìhín yìí fún ìgbà díẹ̀ nítorí ìyàn náà mú púpọ̀ ní ilẹ̀ Kénánì, àwọn ohun-ọ̀sìn àwa ìránṣẹ́ rẹ kò sì rí ewéko jẹ. Nítorí náà jọ̀wọ́ má sàì jẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ rẹ tẹ̀dó sí ilẹ̀ Gósénì.”

5. Fáráò wí fún Jósẹ́fù pé, “Baba rẹ àti àwọn arákùnrin rẹ tọ̀ ọ́ wá,

6. Ilẹ̀ Éjíbítì sì nìyí níwájú rẹ: Mú àwọn arákùnrin rẹ tẹ̀dó sí ibi tí ó dára jù nínú ilẹ̀ náà. Jẹ́ kí wọn máa gbé ní Gósénì. Bí o bá sì mọ ẹnikẹ́ni nínú wọn tí ó ní ẹ̀bùn-ìtọ́jú ẹran, fi wọ́n ṣe olùtọ́jú ẹran-ọ̀sìn mi.”

7. Nígbà náà ni Jósẹ́fù mú Jákọ́bù baba rẹ̀ wọlé wá sí iwájú Fáráò. Lẹ́yìn ìgbà tí Jákọ́bù súre fún Fáráò tán.

8. Fáráò béèrè pé, “Ọmọ ọdún mélòó ni ọ́?”

Jẹ́nẹ́sísì 47