19. “A pàṣẹ fún ọ láti sọ fún wọn pé, ‘Ẹ ṣe èyí: Ẹ mú kẹ̀kẹ́ ẹrù láti ilẹ̀ Éjíbítì fún àwọn ọmọ yín àti àwọn aya yín. Kí ẹ sì mú baba yín tọ mí wá.
20. Ẹ má ṣe àníyàn nípa ohun-ìní yín nítorí èyí tí ó dára jù nínú ilẹ̀ Éjíbítì yóò jẹ́ tiyín.’ ”
21. Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sì ṣe èyí. Jósẹ́fù fún wọn ni kẹ̀kẹ́ ẹrù bí Fáráò ti pàṣẹ, ó sì fún wọn ní oúnjẹ fún ìrìn-àjò wọn pẹ́lú.
22. Ó fún ẹni kọ̀ọ̀kan wọn ní aṣọ tuntun. Ṣùgbọ́n Bẹ́ńjámínì ni ó fún ní ọ̀ọ́dúnrún ẹyọ owó (300) idẹ fàdákà àti ìpààrọ̀ aṣọ márùn ún.