Jẹ́nẹ́sísì 37:11-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì ń ṣe ìlara rẹ̀ ṣugbọ́n baba rẹ̀ pa ọ̀rọ̀ náà mọ́ lọ́kàn rẹ̀.

12. Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì da ẹran baba wọn lọ sí Ṣékémù.

13. Ísírẹ́lì sì wí fún Jósẹ́fù pé, “Ṣé o mọ̀ pé, àwọn arákunrin rẹ ń da ẹran ní Ṣékémù, wá, jẹ́ kí n rán ọ sí wọn.”Jósẹ́fù sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”

14. O sì wí fún un pé, “Lọ wò bí àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn agbo ẹran bá wà ní àlàáfíà, kí o sì wá jíṣẹ́ fún mi.” Ó sì rán Jósẹ́fù lọ láti àfonífojì Ébúrónì.Nígbà tí Jósẹ́fù dé Ṣékémù,

15. Ọkùnrin kan sì rí i tí ó ń rìn kiri inú pápá, ó sì bi í pé, “Kín ni ò ń wá?”

16. Ó sì dáhùn pé, “Àwọn arákùnrin mi ni mò ń wá, ǹjẹ́ o mọ ibi tí wọ́n wà pẹ̀lú agbo ẹran?”

Jẹ́nẹ́sísì 37