Jẹ́nẹ́sísì 36:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Wọ̀nyí ni ìran Ísọ̀, ẹni tí a ń pè ní Édómù.

2. Nínú àwọn ọmọbìnrin Kénánì ni Ísọ̀ ti fẹ́ àwọn ìyàwó rẹ̀: Ádà ọmọbìnrin Élónì ará Hítì àti Óhólíbámà, ọmọbìnrin Ánà, ọmọ ọmọ Ṣíbéónì ará Hífítì.

3. Ó sì tún fẹ́ Báṣémátì ọmọ Ísímáélì arábìnrin Nébájótù.

4. Ádà bí Élífásì fún Ísọ̀, Báṣémátì sì bí Réúẹ́lì,

Jẹ́nẹ́sísì 36