12. Nígbà náà ni Ísọ̀ wí pé, “Jẹ́ kí a máa lọ, n ó sìn ọ.”
13. Ṣùgbọ́n Jákọ́bù wí fún un pé, “Ṣe ìwọ náà ṣe àkíyèsí pé ọ̀pọ̀ nínú àwọn ọmọ wọ̀nyí kéré, àwọn màlúù àti àgùntàn pẹ̀lú sì ní àwọn ọmọ kéékèèké. Bí a bá dà wọ́n rìn jìnnà ju bí agbára wọn se mọ lọ, wọ́n lè kú.
14. Èmi bẹ̀ ọ́, máa lọ ṣíwájú ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ó sì máa rọra bọ̀, títí èmi àti àwọn ọmọ yóò fi dé ọdọ̀ olúwa mi ní Ṣéírì.”
15. Ísọ̀ wí pé, “Jẹ́ kí n fi díẹ̀ sílẹ̀ fún ọ nínú àwọn ọkùnrin mi nígbà náà.”Jákọ́bù wí pé, “Èéṣe, àní kí n sáà rí ojú rere olúwa mi?”
16. Ní ọjọ́ náà gan-an ni Ísọ̀ padà lọ sí Ṣéírì.
17. Jákọ́bù sì lọ sí Ṣúkótù, ó sì kọ́ ilé fún ara rẹ̀, ó sì ṣe ọgbà fún àwọn ẹran. Ìdí èyí ní a fi ń pe ibẹ̀ ní Ṣúkótù.
18. Lẹ́yìn ìgbà tí Jákọ́bù tí Padani-Árámù dé: Àlàáfíà ni Jákọ́bù dé ìlú Sẹ́kẹ́mù ní ilẹ̀ Kénánì, ó sì pàgọ́ sí ìtòòsí ìlú náà.
19. Ó sì ra ilẹ̀ kan tí ó pàgọ́ sí ni ọgọ́rùn-ún owó fàdákà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Hámórì tíí ṣe bàbá Sẹ́kẹ́mù.
20. Níbẹ̀ ni ó gbé tẹ́ pẹpẹ kan tí ó pè ní El Elohe Ísírẹ́lì (Ọlọ́run Ísírẹ́lì).