Jẹ́nẹ́sísì 31:46-50 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

46. Ó sì wí fún àwọn ìbátan rẹ̀ pé, “Ẹ kó àwọn òkúta díẹ̀ jọ.” Wọ́n sì kó òkúta náà jọ bí òkítì wọ́n sì jẹun níbẹ̀.

47. Lábánì sì pe orúkọ rẹ̀ ní Akojọ òkítì ẹ̀rí, ṣùgbọ́n Jákọ́bù pè é ni Gálíídì.

48. Lábánì sì wí pé, “Òkítì yìí jẹ́ ẹ̀rí láàrin èmi àti ìwọ ní òní.” Ìdí nìyí tí a fi pe orúkọ rẹ̀ ni Gálíídì.

49. Ó tún pè é ni Mísípà nítorí, ó wí pé, “Kí Olúwa kí ó máa sọ́ èmi àti ìwọ nígbà tí a bá yà kúrò lọ́dọ̀ ara wa tán.

50. Bí o bá fìyà jẹ àwọn ọmọbìnrin mi, tàbí tí o fẹ́ aya mìíràn yàtọ̀ sí wọn, rántí pé, Ọlọ́run ń bẹ láàrin wa bí ẹlẹ́rìí bí ẹnikẹ́ni kò tilẹ̀ sí.”

Jẹ́nẹ́sísì 31