Jẹ́nẹ́sísì 30:27-36 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

27. Ṣùgbọ́n Lábánì wí fún un pé, “Bí o bá ṣe pé mo rí ojúrere rẹ, jọ̀wọ́ dúró, nítorí, mo ti ṣe àyẹ̀wò rẹ, mo sì rí i pé Olúwa bùkún mi nítorí rẹ.

28. Sọ ohun tí o fẹ́ gẹ́gẹ́ bí owó iṣẹ́ ẹ̀ rẹ, èmi yóò sì san án.”

29. Jákọ́bù sì wí fún un pé, “Ìwọ sá à mọ bí mo ti ṣiṣẹ́ sìn ọ́ àti bí ẹran ọ̀sìn rẹ ti pọ̀ si lábẹ́ ìtọ́jú mi.

30. Ìwọ̀nba díẹ̀ sá à ni o ní kí èmi tó dé, ó sì ti pọ̀ sí i gidigidi, Olúwa sì ti bùkún ọ nínú gbogbo èyí tí mo ṣe. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, nígbà wo ní èmi yóò pèsè fún ìdílé tèmi.”

31. Ó sì tún béèrè wí pé, “Kín ni kí èmi ó fi fún ọ?”Jákọ́bù dáhùn pé, “Má fun mi ni ohunkóhun, ṣùgbọ́n bí ìwọ yóò bá ṣe ohun tí mo fẹ́ sọ yìí, èmi yóò sì máa bá ọ tọ́jú àwọn agbo ẹran rẹ, èmi yóò sì máa bọ́ wọn.

32. Jẹ́ kí èmi kí ó la agbo ẹran kọjá ní òní, èmi yóò sì mú gbogbo àgùntàn onílà àti èyí tí ó ní àmì, àti gbogbo àgbò dúdú pẹ̀lú ewúrẹ́ onílà tàbí tí ó ní àmì. Àwọn wọ̀nyí ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ mi.

33. Òtítọ́ inú mi yóò sì jẹ́rìí fún mi ní ọjọ́ iwájú nígbà tí ìwọ bá wo owó-iṣẹ́ mi tí ìwọ san fún mi, yóò sì ṣe pé gbogbo èyí tí kì í bá ṣe onílà tàbí alámì nínú ewúrẹ́ tàbí tí kì í ṣe dúdú nínú àgùntàn, tí o bá rí ni ọ̀dọ̀ mi ni kí o kà sí mi lọ́rùn pé jíjí ni mo jí i gbé.”

34. Lábánì sì dáhùn pé, “Mo faramọ́ ọn, ṣe bí ìwọ ti wí”

35. Ní ọjọ́ náà gan-an ni Lábánì kó gbogbo ewúrẹ̀ tí ó lámì tàbí ilà (àti akọ àti abo, tí ó ní funfun díẹ̀ lára), pẹ̀lú gbogbo àgbò dúdú, ó sì fi wọ́n sí ìtọ́jú àwọn ọmọ rẹ̀.

36. Ibi tí Lábánì àti Jákọ́bù sì wà sí ara wọn, sì tó ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Jákọ́bù sì ń tọ́jú agbo ẹran Lábánì tí ó kù.

Jẹ́nẹ́sísì 30