Jẹ́nẹ́sísì 24:25-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

25. Ó sì fi kún un pé, “A ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ koríko àti oúnjẹ fún àwọn ràkunmí yín àti yàrá pẹ̀lú fún-un yín láti wọ̀ sí.”

26. Nígbà náà ni ọkùnrin náà tẹríba, ó sì sin Olúwa.

27. Wí pe, “Ògo ni fún Olúwa, Ọlọ́run Ábúráhámù olúwa mi ti kò jẹ́ kí àánú àti òtítọ́ rẹ̀ kí ó yẹ̀ lọ́dọ̀ olúwa mi. Ní ti èmi Olúwa ti darí ìrìn-àjò mi sí ilé ìbátan olúwa mi.”

28. Ọmọbìnrin náà sì sáré, ó sì lọ sọ ohun gbogbo wọ̀nyí fún àwọn ará ilé ìyá rẹ̀.

29. Rèbékà ní arákùnrin tí ń jẹ́ Lábánì; Lábánì sì sáré lọ bá ọkùnrin náà ní etí odò.

Jẹ́nẹ́sísì 24