Jẹ́nẹ́sísì 23:7-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Nígbà náà ni Ábúráhámù dìde, ó sì tẹríba níwájú àwọn ará ilẹ̀ náà-àwọn ará Hítì.

8. Ó sì wí fún wọn pé, “Bí ó bá ṣe pé, lóòótọ́ ni ẹ fẹ́ kí n sin òkú mi kúrò nílẹ̀, ẹ gbọ́ tèmi, ẹ bá mi bẹ Éfúrónì ọmọ Ṣóhárì,

9. kí ó ta ihò àpáta Mákípélà tí ó jẹ́ tirẹ̀ fún mi, èyí tí ó wà ni orí oko rẹ̀, kí ó tà á fún mi ni iye owó tí à ń ta irú rẹ̀ fún ilẹ̀ ìsìnkú láàrin yín.”

10. Éfúrónì ará Hítì sì wà níbẹ̀ pẹ̀lú, ó sì dá Ábúráhámù lóhùn lójú gbogbo àwọn ará ìlú tí ó wà níbẹ̀, lẹ́nu ibodè ìlú,

11. pé, “Rárá, Olúwa mi, Gbọ́ tèmi; mo fún ọ ní ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà níbẹ̀. Mo fún ọ níwájú gbogbo àwọn ènìyàn mi. Sin òkú rẹ ṣíbẹ̀.”

12. Ábúráhámù sì tún tẹríba níwájú àwọn ènìyàn ìlú náà,

Jẹ́nẹ́sísì 23