5. Àwọn ará Hítì dá a lóhùn pé,
6. “Olúwa mi, gbọ́ tiwa, ó jẹ́ alágbára ọmọ-aládé láàrin wa, sin òkú rẹ sí ibojì tí ó dárajù nínú àwọn ibojì wa, kò sí ẹni tí yóò fi ibojì rẹ dùn ọ́ láti sin òkú rẹ sí.”
7. Nígbà náà ni Ábúráhámù dìde, ó sì tẹríba níwájú àwọn ará ilẹ̀ náà-àwọn ará Hítì.
8. Ó sì wí fún wọn pé, “Bí ó bá ṣe pé, lóòótọ́ ni ẹ fẹ́ kí n sin òkú mi kúrò nílẹ̀, ẹ gbọ́ tèmi, ẹ bá mi bẹ Éfúrónì ọmọ Ṣóhárì,
9. kí ó ta ihò àpáta Mákípélà tí ó jẹ́ tirẹ̀ fún mi, èyí tí ó wà ni orí oko rẹ̀, kí ó tà á fún mi ni iye owó tí à ń ta irú rẹ̀ fún ilẹ̀ ìsìnkú láàrin yín.”