Jẹ́nẹ́sísì 22:9-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Nígbà tí wọn sì dé ibi tí Ọlọ́run sọ fún Ábúráhámù, ó mọ pẹpẹ kan, ó sì to igiọ lé e lórí, ó sì di Ísáákì ọmọ rẹ̀, ó sì da dùbúlẹ̀ lórí pẹpẹ náà.

10. Ábúráhámù sì nawọ́ mú ọ̀bẹ, láti dúńbú ọmọ rẹ̀.

11. Ṣùgbọ́n ańgẹ́lì Olúwa ké sí i láti ọ̀run wí pé “Ábúráhámù! Ábúráhámù!”Ábúráhámù sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”

12. Ańgẹ́lì Olúwa sì wí pé, “Má ṣe fọwọ́ kan ọmọ náà, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ṣe é ni ohun kan. Nísinsin yìí ni mo mọ̀ pé o bẹ̀rù Ọlọ́run, nítorí pé ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan soso dùn mi.”

13. Ábúráhámù sì gbójú sókè, ó sì rí àgbò kan tí ó fi ìwo há pàǹtírí, ó sì lọ mú un, ó sì fi rú ẹbọ ṣíṣun, dípò ọmọ rẹ̀.

14. Ábúráhámù sì pe orúkọ ibẹ̀ ni, Olúwa yóò pèṣè (Jìhófà Jirè). Bẹ́ẹ̀ ni a sì ń wí títí di òní olónìí pé, “Ní orí òkè Olúwa, ni a ó ti pèsè.”

15. Ańgẹ́lì Olúwa sì tún pe Ábúráhámù láti ọ̀run lẹ́ẹ̀kejì.

16. Ó sì wí pé, Olúwa wí pé, “Mo fi ara mi búra, níwọ̀n bí ìwọ ti ṣe èyí, tí ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dùn mí,

Jẹ́nẹ́sísì 22