Jẹ́nẹ́sísì 20:16-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Ábímélékì sì wí fún Ṣárà pé, “Mo fi ẹgbẹ̀rún owó ẹyọ fàdákà fún arákùnrin rẹ. Éyí ni owó ìtanràn ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ọ níwájú gbogbo ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ àti pé, a dá ọ láre pátapáta.”

17. Nígbà náà, Ábúráhámù gbàdúrà sí Ọlọ́run, Ọlọ́run sì wo Ábímélékì àti aya rẹ̀ àti àwọn ẹrúbìnrin rẹ̀ sàn. Wọ́n sì tún ń bímọ.

18. Nítorí Ọlọ́run ti ṣé gbogbo ará ilé Ábímélékì nínú nítorí Sárà aya Ábúráhámù.

Jẹ́nẹ́sísì 20