16. Ábímélékì sì wí fún Ṣárà pé, “Mo fi ẹgbẹ̀rún owó ẹyọ fàdákà fún arákùnrin rẹ. Éyí ni owó ìtanràn ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ọ níwájú gbogbo ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ àti pé, a dá ọ láre pátapáta.”
17. Nígbà náà, Ábúráhámù gbàdúrà sí Ọlọ́run, Ọlọ́run sì wo Ábímélékì àti aya rẹ̀ àti àwọn ẹrúbìnrin rẹ̀ sàn. Wọ́n sì tún ń bímọ.
18. Nítorí Ọlọ́run ti ṣé gbogbo ará ilé Ábímélékì nínú nítorí Sárà aya Ábúráhámù.