Jẹ́nẹ́sísì 14:18-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Mélíkísédékì ọba Ṣálẹ́mù (Jérúsálẹ́mù) sì mú oúnjẹ àti ọtí wáìnì jáde wá. Òun ni àlùfáà Ọlọ́run, ọ̀gá ògo.

19. Ó sì súre fún Ábúrámù wí pé,“Ìbùkún ni fún Ábúrámù láti ọ̀dọ̀Ọlọ́run ọ̀gá ògo tí ó dá ọ̀run òun ayé.

20. Ìbùkún sì ni fún Ọlọ́run ọ̀gá ògojùlọ tí ó fi àwọn ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́.”Ábúrámù sì fún un ní ìdámẹ́wàá ohun gbogbo.

21. Ọba Ṣódómù sì wí fún Ábúrámù pé, “Kó àwọn ènìyàn mi fún mi, ṣùgbọ́n mú àwọn ẹrù fún ara rẹ.”

Jẹ́nẹ́sísì 14