9. Ojú mi kò ní i dá ọ sí, ń kò sì ní wò ọ́ pẹ̀lú àánú; ń o san-an fún ọ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀nà ìwà àti gbogbo ìwà ìríra tí wà láàrin rẹ. Nígbà náà ní ẹ o mọ̀ pé èmi Olúwa lo kọlù yín.
10. “Ọjọ́ náà ti dé! O ti dé: Ìparun ti bú jáde, ọ̀pá ti tan ná, ìgbéraga ti sọ jáde!
11. Ìwà ipá ti di ọ̀pá ìwà búburú; kò sí nínú wọn tí yóò ṣẹ́kú, tàbí nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn, kò sí ọrọ̀ ko si ohun ti o niye.
12. Àsìkò náà ti tó; ọjọ́ náà tidé, kí ẹni tó n rajà má se yọ̀ bẹ́ẹ̀ ni ki ontàjà má ṣe ṣọ̀fọ̀; torí, ìbínú gbígbóná wà lórí gbogbo ènìyàn.