Ísíkẹ́lì 7:1-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:

2. “Ọmọ, ènìyàn báyìí ni Olúwa Ọlorún wí sí ilé Ísírélì: Òpin! Òpin ti dé sí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilẹ̀ náà.

3. Òpin tí dé sí ọ báyìí n ó sì tú ìbínú mi jáde sí ọ, n ó dájọ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìwà rẹ, ń ó sì san-an fún ọ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìwà ìríra rẹ.

4. Ojú mi kò ní i dá ọ sì bẹ́ẹ̀ ni ń kò sì ní wò ọ́ pẹ̀lú àánú; ṣùgbọ́n ń ó san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti gbogbo ìwà ìríra tó wà láàrin rẹ. Nígbà náà ní ẹ o mọ̀ pé èmi ni Olúwa.

5. “Èyí ni Olúwa Ọlọ́run wí: Àjálù, àjálù lórí àjálù ń bọ̀;

6. Òpin ti dé! Òpin ti dé, ó ti dìde lòdì sí ọ. Ó ti dé!

7. Ìparun ti dé sórí yín gbogbo, ẹ̀yin tó ń gbé ní ilẹ̀ náà. Àsìkò ti tó, ọjọ́ wàhálà ti súnmọ́ etílé; kì í ṣe ọjọ́ ariwo ayọ̀ lórí òkè.

8. Mo ṣetán láti tú ìbìnú gbígbóná mi lé ọ lórí àti láti lo ìbínú mi lórí rẹ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀nà rẹ, n ó sì san án fún ọ gẹ́gẹ́ bi gbogbo ìwà ìríra rẹ.

9. Ojú mi kò ní i dá ọ sí, ń kò sì ní wò ọ́ pẹ̀lú àánú; ń o san-an fún ọ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀nà ìwà àti gbogbo ìwà ìríra tí wà láàrin rẹ. Nígbà náà ní ẹ o mọ̀ pé èmi Olúwa lo kọlù yín.

10. “Ọjọ́ náà ti dé! O ti dé: Ìparun ti bú jáde, ọ̀pá ti tan ná, ìgbéraga ti sọ jáde!

11. Ìwà ipá ti di ọ̀pá ìwà búburú; kò sí nínú wọn tí yóò ṣẹ́kú, tàbí nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn, kò sí ọrọ̀ ko si ohun ti o niye.

12. Àsìkò náà ti tó; ọjọ́ náà tidé, kí ẹni tó n rajà má se yọ̀ bẹ́ẹ̀ ni ki ontàjà má ṣe ṣọ̀fọ̀; torí, ìbínú gbígbóná wà lórí gbogbo ènìyàn.

13. Nítorí pé ontàjà kò ni ri ilé tó tà gbà níwọ̀n ìgbà ti awọ̀n méjèèjì bá wà láyé; torí ìran tó kan ènìyàn yìí kò ní yí padà. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, kò sí ọ̀kan nínú wọn tí yóò gba ara rẹ̀ là.

Ísíkẹ́lì 7