1. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé:
2. “Ọmọ ènìyàn, dojú kọ àwọn òkè Ísírẹ́lì; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí wọn
3. wí pé: ‘Ẹ̀yin òkè Ísírẹ́lì, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run. Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run wí sí ẹ̀yin òkè ńlá àti àwọn òkè kékèké sí àwọn odò ṣíṣàn àti sí àfonífojì, n ó mú idà wa sórí yín, n ó sì pa ibi gíga yín run.