Ísíkẹ́lì 44:14-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Síbẹ̀ èmi yóò mu wọn sí ìtọ́jú ilé Ọlọ́run àti gbogbo isẹ́ tí a gbọdọ̀ se níbẹ̀.

15. “ ‘Ṣùgbọ́n àwọn àlùfáà, tí ó jẹ́ Léfì àti àwọn ìran Sádómù tí fi tọkàntọkàn ṣe iṣẹ́ ibi mímọ́ mi nígbà tí àwọn Ísírẹ́lì ṣáko lọ kúrò lọ́dọ̀ mi, wọn gbọdọ̀ súnmọ́ iwájú láti ṣe ìránṣẹ́ ní iwájú mi, láti rú ẹbọ ọ̀rá àti ẹ̀jẹ̀, ni Olúwa Ọba sọ.

16. Àwọn nìkan ni ó gbọdọ̀ wọ ibi mímọ́ mi; àwọn nìkan ní o gbọdọ̀ sùnmọ́ tábìlì mi láti ṣe ìránṣẹ́ ni iwájú mi, ki wọn sì ṣe iṣẹ́ ìsìn mi.

17. “ ‘Nígbà ti wọ́n wọ àwọn ẹnu ọ̀nà àgbàlá ti inú, wọn yóò wọ aṣọ ọ̀gbọ̀, wọn kò gbọdọ̀ wọ aṣọ onírun nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní àwọn ẹnu ọ̀nà àgbàlá ti inú tàbí ni inú ilé Ọlọ́run.

18. Wọ́n ní láti dé fìlà ọ̀gbọ̀ sí orí wọn àti àwọ̀tẹ́lẹ̀ ọ̀gbọ̀ sí ìdí wọn. Wọn kò gbọdọ̀ wọ ohunkóhun tí yóò mú wọn làágùn.

Ísíkẹ́lì 44