Ísíkẹ́lì 40:47-49 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

47. Ó sì wọn àgbàlá náà, ọgọ́rùn ún ìgbọ̀nwọ́ ni gígùn, ọgọ́rùn ún ìgbọ̀nwọ́ ni ìbú, igun mẹ́rin lọ́gbọọgba, àti pẹpẹ ti ń bẹ níwájú ilé náà.

48. Ó mú mi lọ sí àtẹ̀wọ̀ ẹnu ọ̀nà tẹ́ḿpìlì, ó sì wọn àwọn àtẹrígbà àtẹ̀wọ̀ ẹnu ọ̀nà; wọ́n jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn ún ní fífẹ̀, ẹ̀gbẹ́ méjèèjì rẹ̀. Fífẹ̀ àbáwọlé jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rìnlá, ìgbéró àwọn ògiri náà jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ta ní fífẹ̀ ní ẹ̀gbẹ́ méjèèjì.

49. Àtẹ̀wọ̀ ẹnu ọ̀nà jẹ́ ogún ìgbọ̀nwọ́ ní fífẹ̀, àti ìgbọ̀nwọ́ méjìlá láti iwájú dé ẹ̀yìn. Láti ara àtẹ̀gùn ní a ti ń dé ibẹ̀ àwọn òpó sì wà ni ẹ̀gbẹ́ kọ̀ọ̀kan àwọn àtẹ́rígbà náà.

Ísíkẹ́lì 40