12. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi Olúwa ti gbọ gbogbo ohun ẹ̀gàn tí ìwọ ti sọ lòdì sí àwọn òkè Ísírẹ́lì náà. Ìwọ wí pé, “A ti fi wọ́n sílẹ̀ ní ṣíṣọ̀fọ̀, a sì fi fún wa láti pajẹ.”
13. Ìwọ lérí sí mi, ó sì sọ̀rọ̀ lòdì sí mí láìsí ìdádúró, èmi sì gbọ́ ọ.
14. Èyí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: Nígbà tí gbogbo ayé bá ń yọ̀, èmi yóò mú kí ó di ahoro
15. Nítorí pé ìwọ ń yọ̀ nígbà tí ìní ilé Ísírẹ́lì di ahoro, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni èmi yóò ṣe hùwà sí ọ. Ìwọ yóò di ahoro, ìwọ òkè Séírì, ìwọ àti gbogbo ará Édómù. Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa.’ ”