Ísíkẹ́lì 33:26-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

26. Ẹ̀yin gbẹ́kẹ̀lé idà yín, ẹ̀yin ṣe nǹkan ìríra, ẹnì kọ̀ọ̀kan nínú yín baa obìnrin aládúgbò rẹ̀ jẹ́. Ẹ̀yin yóò ha gba ilẹ̀ náà?’

27. “Sọ èyí fún wọn: ‘Èyí yìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: Bí mo ti wà láààyè, àwọn tí ó kúrò nínú ìparun yóò ti ipa idà ṣubú, àwọn tí ẹranko búburú yóò pajẹ, àwọn tí ó sì wà ní ilé ìsọ àti inú ihò òkúta ni àjàkálẹ̀-àrùn yóò pa.

28. Èmi yóò mú kí ilẹ náà di ahoro, agbára ìgbéraga rẹ̀ yóò sì di ahoro kí ẹnikẹ́ni má ṣe ré wọn kọjá.

Ísíkẹ́lì 33