32. “Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè:“Ìwọ yóò mu nínú aago ẹ̀gbọ́n rẹ,aago tí ó tóbi tí ó sì jinnú:yóò mú ìfisẹ̀sín àti ìfiṣe ẹlẹ́yà wá,nítorí tí aago náà gba nǹkan púpọ̀.
33. Ìwọ yóò mu àmupara àti ìbànújẹ́,aago ìparun àti ìsọdahoroaago ẹ̀gbọ́n rẹ Samaríà.
34. Ìwọ yóò mú un, ni àmugbẹ;ìwọ yóò sì fọ sí wẹ́wẹ́ìwọ yóò sì fa ọmú rẹ̀ ya.Èmi ti sọ̀rọ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.